Esek 32:19-23 Yorùbá Bibeli (YCE)

19. Tani iwọ julọ li ẹwà? sọkalẹ, ki a si tẹ́ ọ tì awọn alaikọla.

20. Nwọn o ṣubu li ãrin awọn ti a fi idà pa: a fi on le idà lọwọ: fà a, ati awọn ọ̀pọlọpọ enia rẹ̀.

21. Awọn alagbara lãrin awọn alagbara yio sọ̀rọ si i lati ãrin ipò-okú wá, pẹlu awọn ti o ràn a lọwọ: nwọn sọkalẹ lọ, nwọn dubulẹ, awọn alaikọla ti a fi idà pa.

22. Assuru wà nibẹ̀ ati gbogbo ẹgbẹ́ rẹ̀: awọn ibojì rẹ̀ wà lọdọ rẹ̀: gbogbo wọn li a pa, ti o ti ipa idà ṣubu:

23. Ibojì awọn ẹniti a gbe kà ẹgbẹ́ ihò, awọn ẹgbẹ́ rẹ̀ si yi ibojì rẹ̀ ka, gbogbo wọn li a pa, nwọn ti ipa idà ṣubu, ti o da ẹ̀ru silẹ ni ilẹ alãye.

Esek 32