Esek 32:16-20 Yorùbá Bibeli (YCE)

16. Eyi ni ohùn-rére, nwọn o si pohùnrére rẹ̀: awọn ọmọbinrin awọn orilẹ-ède yio pohùnrére rẹ̀: nwọn o pohùnrére nitori rẹ̀, ani fun Egipti, ati gbogbo ọ̀pọlọpọ enia rẹ̀, li Oluwa Ọlọrun wi.

17. O si tun ṣe li ọdun kejila, li ọjọ kẹ̃dogun oṣù, ọ̀rọ Oluwa tọ̀ mi wá, wipe.

18. Ọmọ enia, pohùnrére fun ọ̀pọlọpọ enia Egipti, ki o si sọ̀ wọn kalẹ, on, ati awọn ọmọbinrin orilẹ-ède olokiki, si ìsalẹ aiye, pẹlu awọn ti o sọkalẹ lọ sinu ihò.

19. Tani iwọ julọ li ẹwà? sọkalẹ, ki a si tẹ́ ọ tì awọn alaikọla.

20. Nwọn o ṣubu li ãrin awọn ti a fi idà pa: a fi on le idà lọwọ: fà a, ati awọn ọ̀pọlọpọ enia rẹ̀.

Esek 32