Esek 32:1-7 Yorùbá Bibeli (YCE)

1. O si ṣe li ọdun kejila, li oṣù kejila, li ọjọ ikini oṣù, ọ̀rọ Oluwa tọ̀ mi wá, wipe,

2. Ọmọ enia, pohunrére fun Farao ọba Egipti, si wi fun u pe, Iwọ dabi ẹgbọ̀rọ kiniun awọn orilẹ-ède, iwọ si dabi dragoni ninu okun, iwọ si jade wá pẹlu awọn odò rẹ, iwọ ti fi ẹsẹ rẹ rú omi, o si ti bà awọn odò wọn jẹ́.

3. Bayi li Oluwa Ọlọrun wi; Nitorina emi o nà àwọn mi sori rẹ pẹlu ẹgbẹ́ enia pupọ̀; nwọn o si fà ọ goke ninu àwọn mi.

4. Nigbana ni emi o fi ọ silẹ lori ilẹ, emi o gbe ọ sọ sinu igbẹ́, emi o mu ki gbogbo awọn ẹiyẹ oju ọrun ba le ọ lori, emi o si fi ọ bọ́ gbogbo awọn ẹranko aiye.

5. Emi o gbe ẹran ara rẹ kà awọn ori oke, gbogbo afonifoji li emi o fi giga rẹ kún.

6. Emi o si fi ẹ̀jẹ rẹ rin ilẹ nibiti iwọ nluwẹ́, ani si awọn oke; awọn odò yio si kún fun ọ.

7. Nigbati emi o ba mú ọ kuro, emi o bò ọrun, emi o si mu ki awọn ìrawọ inu rẹ̀ ṣokùnkun, emi o fi kũkũ bò õrùn, òṣupa kì yio si fi imọlẹ rẹ̀ hàn.

Esek 32