Esek 3:20-27 Yorùbá Bibeli (YCE)

20. Ẹ̀wẹ, nigbati olododo ba yipada kuro ninu ododo rẹ̀, ti o si da ẹ̀ṣẹ, ti mo si fi ohun idigbolu siwaju rẹ, yio kú; nitoriti iwọ kò kilọ fun u, yio kú ninu ẹ̀ṣẹ rẹ̀, a ki yio ranti ododo rẹ̀ ti o ti ṣe; ṣugbọn ẹjẹ rẹ̀ li emi o bere li ọwọ́ rẹ.

21. Ṣugbọn bi iwọ ba kilọ fun olododo, ki olododo ki o má dẹ̀ṣẹ, ti on kò si ṣẹ̀, yio yè nitotọ, nitori ti a kilọ fun u, ọrùn rẹ si mọ́.

22. Ọwọ́ Oluwa si wà lara mi nibẹ; o si wi fun mi pe, Dide, lọ si pẹtẹlẹ, emi o si ba ọ sọ̀rọ nibẹ.

23. Mo si dide, mo si lọ si pẹtẹlẹ, si kiyesi i ogo Oluwa duro nibẹ, bi ogo ti mo ri lẹba odò Kebari: mo si doju mi bolẹ.

24. Ẹmi si wọ̀ inu mi lọ, o si gbe mi duro li ẹsẹ mi, o si ba mi sọ̀rọ, o si sọ fun mi pe, Lọ, há ara rẹ mọ ile rẹ.

25. Ṣugbọn iwọ, ọmọ enia, kiyesi i, nwọn o si fi idè le ọ, nwọn o si fi dè ọ, iwọ ki yio si jade larin wọn.

26. Emi o si mu ahọn rẹ lẹ mọ oke ẹnu rẹ, iwọ o si yadi, iwọ ki yio jẹ abaniwi si wọn; nitori ọlọ̀tẹ ile ni nwọn.

27. Ṣugbọn nigbati mo ba bá ọ sọ̀rọ, emi o ya ẹnu rẹ, iwọ o si wi fun wọn pe, Bayi li Oluwa Ọlọrun wi; Ẹniti o gbọ́, jẹ ki o gbọ́; ẹniti o kọ̀, jẹ ki o kọ̀ nitori ọlọ̀tẹ ile ni nwọn.

Esek 3