Esek 24:1-5 Yorùbá Bibeli (YCE)

1. Ọ̀RỌ Oluwa tun tọ̀ mi wá, li ọdun kẹsan, li oṣu kẹwa, li ọjọ kẹwa oṣu, wipe,

2. Ọmọ enia, iwọ kọ orukọ ọjọ na, ani ọjọ kanna yi: ọba Babiloni doju kọ Jerusalemu li ọjọ kanna yi:

3. Si pa owe si ọlọtẹ ilẹ na, si wi fun wọn pe, Bayi li Oluwa Ọlọrun wi: Gbe ìkoko ka iná, gbe e kà a, si dà omi sinu rẹ̀ pẹlu:

4. Kó aján na jọ sinu rẹ̀, olukuluku aján ti o tobi, itan, ati apá, fi egungun ti o jọju kún inu rẹ̀.

5. Mu ninu agbo-ẹran ti o jọju, ko awọn egungun sabẹ rẹ̀, si jẹ ki o hó dãdã, si jẹ ki nwọn bọ̀ egungun rẹ̀ ninu rẹ̀.

Esek 24