Esek 23:45-49 Yorùbá Bibeli (YCE)

45. Ati awọn ọkunrin olododo, nwọn o ṣe idajọ wọn, bi a ti iṣe idajọ awọn àgbere obinrin, ati bi a ti iṣe idajọ awọn obinrin ti o ta ẹjẹ silẹ; nitoripe àgbere ni nwọn, ẹjẹ si wà lọwọ wọn.

46. Nitori bayi li Oluwa Ọlọrun wi; emi o mu ẹgbẹ kan tọ̀ wọn wá, emi o si fi wọn fun wọn lati kó wọn lọ, ati lati bà wọn jẹ.

47. Ẹgbẹ na yio si sọ wọn li okuta, nwọn o si fi idà pa wọn; nwọn o pa awọn ọmọ wọn ọkunrin, ati awọn ọmọ wọn obinrin, nwọn o si fi iná kun ile wọn.

48. Bayi li emi o jẹ ki ìwa ifẹkufẹ mọ lãrin ilẹ na, ki a ba le kọ́ gbogbo obinrin, ki nwọn má bà ṣe bi ifẹkufẹ nyin.

49. Nwọn o si san ẹ̀san ìwa ifẹkufẹ nyin si ori nyin, ẹnyin o si rù ẹ̀ṣẹ oriṣa nyin; ẹnyin o si mọ̀ pe emi li Oluwa Ọlọrun.

Esek 23