Esek 23:3-14 Yorùbá Bibeli (YCE)

3. Nwọn si ṣe panṣaga ni Egipti; nwọn ṣe panṣaga nigba ewe wọn: nibẹ ni a tẹ̀ ọmú wọn, nibẹ ni wọn si rin ọmú igbà wundia wọn.

4. Orukọ wọn si ni Ahola, ti iṣe ẹ̀gbọn, ati Aholiba aburo rẹ̀: ti emi si ni nwọn, nwọn si bi ọmọkunrin ati ọmọbinrin. Orukọ wọn ni eyi; Samaria ni Ahola, Jerusalemu si li Aholiba.

5. Ahola si ṣe panṣaga, nigbati o jẹ ti emi; o si fẹ awọn olufẹ rẹ̀ li afẹju, awọn ara Assiria aladugbo rẹ̀,

6. Ti a fi aṣọ alaro bò lara, awọn balogun ati awọn olori, gbogbo nwọn jẹ ọmọkunrin ti o wun ni, awọn ẹlẹṣin ti o ngùn ẹṣin.

7. Bayi li o ṣe panṣaga rẹ̀ pẹlu wọn, pẹlu gbogbo awọn aṣàyan ọkunrin Assiria, ati pẹlu gbogbo awọn ti o fẹ li afẹjù: o fi gbogbo oriṣa wọn ba ara rẹ̀ jẹ.

8. Bẹ̃ni kò fi panṣaga rẹ̀ ti o mu ti Egipti wá silẹ: nitori nigba ewe rẹ̀ ni nwọn ba a sùn, nwọn si rin ọmú ìgba wundia rẹ̀, nwọn si dà panṣaga wọn si i lara.

9. Nitorina ni mo ti fi le ọwọ́ awọn olufẹ rẹ̀, le ọwọ́ awọn ara Assiria, awọn ti o fẹ li afẹju.

10. Awọn wọnyi tu ìhoho rẹ̀ silẹ: nwọn mu awọn ọmọ rẹ̀ ọkunrin ati awọn ọmọ rẹ̀ obinrin, nwọn si fi idà pa a: o si di ẹni-olokiki lãrin awọn obinrin; nitori pe nwọn ti mu idajọ ṣẹ si i lara.

11. Nigbati Aholiba aburo ri eyi, o wà bàjẹ ju on lọ ni ìwa ifẹkufẹ rẹ̀, ati ni panṣaga rẹ̀ ju ẹ̀gbọn rẹ̀ lọ ni panṣaga rẹ̀.

12. O fẹ awọn ara Asiria aludugbo rẹ̀ li afẹju, awọn balogun ati awọn olori, ti a wọ̀ li aṣọ daradara, awọn ẹlẹṣin ti o ngùn ẹṣin, gbogbo wọn jẹ ọmọkunrin ti o wuni.

13. Nigbana ni mo ri pe a bà a jẹ, awọn mejeji gba ọ̀na kan.

14. Ati pe o mu ki panṣaga rẹ̀ bi si i: nitori igbati o ri awọn ọkunrin ti a ṣe li àworan sara ogiri, ere awọn ara Kaldea ti a fi ododó ṣe li àworan,

Esek 23