Esek 23:27-31 Yorùbá Bibeli (YCE)

27. Bayi li emi o jẹ ki ifẹkufẹ rẹ mọ kuro lọdọ rẹ, ati panṣaga rẹ ti o mu ti ilẹ Egipti wá; tobẹ̃, ti iwọ kì yio gboju rẹ soke si wọn, bẹ̃ni iwọ kì yio si ranti Egipti mọ.

28. Nitori bayi li Oluwa Ọlọrun wi; Kiyesi i, emi o fi ọ le awọn ti iwọ korira lọwọ, li ọwọ́ awọn ẹniti ọkàn rẹ ṣi:

29. Nwọn o si ba ọ lo ilo irira, nwọn o si ko gbogbo iṣẹ rẹ lọ, nwọn o si fi ọ silẹ ni ihoho ati ni goloto: ati ihoho panṣaga rẹ li a o tu silẹ, ti ifẹkufẹ rẹ, ati panṣaga rẹ.

30. Emi o ṣe gbogbo nkan wọnyi si ọ, nitori pe iwọ ti bá awọn keferi ṣe agbere lọ, ati pe iwọ ti fi oriṣa wọn bà ara rẹ jẹ́.

31. Iwọ ti rìn li ọ̀na ẹ̀gbọn rẹ, nitorina li emi o fi ago rẹ̀ le ọ lọwọ.

Esek 23