Esek 23:1-9 Yorùbá Bibeli (YCE)

1. Ọ̀RỌ Oluwa tun tọ̀ mi wá, wipe,

2. Ọmọ enia, obinrin meji wà, ọmọbinrin iyá kanna:

3. Nwọn si ṣe panṣaga ni Egipti; nwọn ṣe panṣaga nigba ewe wọn: nibẹ ni a tẹ̀ ọmú wọn, nibẹ ni wọn si rin ọmú igbà wundia wọn.

4. Orukọ wọn si ni Ahola, ti iṣe ẹ̀gbọn, ati Aholiba aburo rẹ̀: ti emi si ni nwọn, nwọn si bi ọmọkunrin ati ọmọbinrin. Orukọ wọn ni eyi; Samaria ni Ahola, Jerusalemu si li Aholiba.

5. Ahola si ṣe panṣaga, nigbati o jẹ ti emi; o si fẹ awọn olufẹ rẹ̀ li afẹju, awọn ara Assiria aladugbo rẹ̀,

6. Ti a fi aṣọ alaro bò lara, awọn balogun ati awọn olori, gbogbo nwọn jẹ ọmọkunrin ti o wun ni, awọn ẹlẹṣin ti o ngùn ẹṣin.

7. Bayi li o ṣe panṣaga rẹ̀ pẹlu wọn, pẹlu gbogbo awọn aṣàyan ọkunrin Assiria, ati pẹlu gbogbo awọn ti o fẹ li afẹjù: o fi gbogbo oriṣa wọn ba ara rẹ̀ jẹ.

8. Bẹ̃ni kò fi panṣaga rẹ̀ ti o mu ti Egipti wá silẹ: nitori nigba ewe rẹ̀ ni nwọn ba a sùn, nwọn si rin ọmú ìgba wundia rẹ̀, nwọn si dà panṣaga wọn si i lara.

9. Nitorina ni mo ti fi le ọwọ́ awọn olufẹ rẹ̀, le ọwọ́ awọn ara Assiria, awọn ti o fẹ li afẹju.

Esek 23