Esek 14:21-23 Yorùbá Bibeli (YCE)

21. Nitori bayi li Oluwa Ọlọrun wi; Melomelo ni nigbati mo ba rán awọn idajọ kikan mi mẹrẹrin sori Jerusalemu, idà, ati iyàn, ati ẹranko buburu, ati ajakalẹ àrun, lati ké enia ati ẹranko kuro ninu rẹ̀?

22. Ṣugbọn kiye si i, ninu rẹ̀ li a o kù awọn ti a o yọ silẹ, ti a o mu jade wá, ati ọmọkunrin, ati ọmọbinrin, kiye si i, nwọn o jade tọ̀ nyin wá, ẹnyin o si ri ọ̀na wọn ati iṣe wọn, a o si tù nyin ninu niti ibi ti emi ti mu wá sori Jerusalemu, ani niti gbogbo ohun ti mo ti mu wá sori rẹ̀.

23. Nwọn o si tù nyin ninu, nigbati ẹnyin ba ri ọ̀na wọn ati iṣe wọn: ẹnyin o si mọ̀ pe emi kò ṣe gbogbo ohun ti mo ti ṣe ninu rẹ̀ li ainidi, ni Oluwa Ọlọrun wi.

Esek 14