Eks 22:19-24 Yorùbá Bibeli (YCE)

19. Ẹnikẹni ti o ba bá ẹranko dàpọ pipa li a o pa a.

20. Ẹnikẹni ti o ba rubọ si oriṣakoriṣa, bikoṣe si JEHOFA nikanṣoṣo, a o pa a run tútu.

21. Iwọ kò gbọdọ ṣìka si alejò, bẹ̃ni iwọ kò gbọdọ ni i lara: nitoripe alejò li ẹnyin ti jẹ́ ni ilẹ Egipti.

22. Ẹnyin kò gbọdọ jẹ opó ni ìya, tabi ọmọ alainibaba.

23. Bi iwọ ba jẹ wọn ni ìyakiya, ti nwọn si kigbe pè mi, emi o gbọ́ igbe wọn nitõtọ.

24. Ibinu mi yio si gboná, emi o si fi idà pa nyin; awọn aya nyin yio si di opó, awọn ọmọ nyin a si di alainibaba.

Eks 22