Deu 5:3-13 Yorùbá Bibeli (YCE)

3. OLUWA kò bá awọn baba wa dá majẹmu yi, bikoṣe awa, ani awa, ti gbogbo wa mbẹ lãye nihin li oni.

4. OLUWA bá nyin sọ̀rọ li ojukoju lori òke na, lati ãrin iná wá,

5. (Emi duro li agbedemeji OLUWA ati ẹnyin ni ìgba na, lati sọ ọ̀rọ OLUWA fun nyin: nitoripe ẹnyin bẹ̀ru nitori iná na, ẹnyin kò si gòke lọ sori òke na;) wipe,

6. Emi li OLUWA Ọlọrun rẹ, ti o mú ọ lati ilẹ Egipti, lati oko-ẹrú jade wá.

7. Iwọ kò gbọdọ ní ọlọrun miran pẹlu mi.

8. Iwọ kò gbọdọ yá ere fun ara rẹ, tabi aworán apẹrẹ kan ti mbẹ loke ọrun, tabi ti mbẹ ni ilẹ nisalẹ, tabi ti mbẹ ninu omi ni isalẹ ilẹ:

9. Iwọ kò gbọdọ tẹ̀ ori rẹ ba fun wọn, bẹ̃ni iwọ kò gbọdọ sìn wọn: nitoripe emi OLUWA Ọlọrun rẹ Ọlọrun owú ni mi, ti mbẹ̀ ẹ̀ṣẹ awọn baba wò lara awọn ọmọ, ati lara iran kẹta ati ẹkẹrin ninu awọn ti o korira mi.

10. Emi a si ma ṣe ãnu fun ẹgbẹgbẹrun awọn ti o fẹ́ mi, ti nwọn si pa ofin mi mọ́.

11. Iwọ kò gbọdọ pè orukọ OLUWA Ọlọrun rẹ li asan: nitoriti OLUWA ki yio mu ẹniti o pè orukọ rẹ̀ li asan bi alailẹṣẹ lọrùn.

12. Kiyesi ọjọ́-isimi lati yà a simimọ́, bi OLUWA Ọlọrun rẹ ti paṣẹ fun ọ.

13. Ijọ́ mẹfa ni iwọ o ṣiṣẹ, ti iwọ o si ṣe iṣẹ rẹ gbogbo:

Deu 5