Deu 23:1-5 Yorùbá Bibeli (YCE)

1. ẸNITI a fọ ni kóro, tabi ti a ke ẹ̀ya ìkọkọ rẹ̀ kuro, ki yio wọ̀ inu ijọ enia OLUWA.

2. Ọmọ-àle ki yio wọ̀ inu ijọ enia OLUWA; ani dé iran kẹwa enia rẹ̀ kan ki yio wọ̀ inu ijọ enia OLUWA.

3. Ọmọ Ammoni tabi ọmọ Moabu kan ki yio wọ̀ inu ijọ enia OLUWA; ani dé iran kẹwa enia wọn kan ki yio wọ̀ inu ijọ enia OLUWA lailai:

4. Nitoriti nwọn kò fi omi pẹlu onjẹ pade nyin li ọ̀na, nigbati ẹnyin nti Egipti jade wá; ati nitoriti nwọn bẹ̀wẹ Balaamu ọmọ Beori ara Petori ti Mesopotamia si ọ, lati fi ọ bú.

5. Ṣugbọn OLUWA Ọlọrun rẹ kò fẹ́ fetisi ti Balaamu; OLUWA Ọlọrun rẹ si yi egún na pada si ibukún fun ọ, nitoriti OLUWA Ọlọrun rẹ fẹ́ ọ.

Deu 23