Deu 10:18-22 Yorùbá Bibeli (YCE)

18. On ni ima ṣe idajọ alainibaba ati opó, o si fẹ́ alejò, lati fun u li onjẹ ati aṣọ.

19. Nitorina ki ẹnyin ki o ma fẹ́ alejò: nitoripe ẹnyin ṣe alejò ni ilẹ Egipti.

20. Ki iwọ ki o ma bẹ̀ru OLUWA Ọlọrun rẹ; on ni ki iwọ ki o ma sìn, on ni ki iwọ ki o si faramọ́, orukọ rẹ̀ ni ki o si ma fi bura.

21. On ni iyìn rẹ, on si li Ọlọrun rẹ, ti o ṣe ohun nla ati ohun ẹ̀lẹru wọnni fun ọ, ti oju rẹ ri.

22. Awọn baba rẹ sọkalẹ lọ si Egipti ti awọn ti ãdọrin enia; ṣugbọn nisisiyi OLUWA Ọlọrun rẹ sọ ọ dabi irawọ ọrun li ọ̀pọlọpọ.

Deu 10