A. Oni 19:1-3 Yorùbá Bibeli (YCE)

1. O si ṣe li ọjọ́ wọnni, nigbati kò sí ọba kan ni Israeli, ọkunrin Lefi kan nṣe atipo ni ìha ọhún ilẹ òke Efraimu, ẹniti o si mú àle kan lati Beti-lehemu-juda wá.

2. Àle rẹ̀ na si ṣe panṣaga si i, o si lọ kuro lọdọ rẹ̀ si ile baba rẹ̀ si Beti-lehemu-juda, o si wà ni ibẹ̀ ni ìwọn oṣù mẹrin.

3. Ọkọ rẹ̀ si dide, o si tọ̀ ọ lọ, lati tù u ninu, ati lati mú u pada, ọmọ-ọdọ rẹ̀ si mbẹ pẹlu rẹ̀, ati kẹtẹkẹtẹ meji: ọmọbinrin na si mú u wá sinu ile baba rẹ̀: nigbati baba rẹ̀ si ri i, o yọ̀ lati pade rẹ̀.

A. Oni 19