17. Àwọn obinrin àdúgbò bá sọ ọmọ náà ní Obedi, wọ́n ń sọ káàkiri pé, “A bí ọmọkunrin kan fún Naomi.” Obedi yìí ni baba Jese tíí ṣe baba Dafidi.
18. Àwọn atọmọdọmọ Peresi nìwọ̀nyí: Peresi ni baba Hesironi;
19. Hesironi bí Ramu, Ramu bí Aminadabu;
20. Aminadabu bí Naṣoni; Naṣoni bí Salimoni;