15. Ọmọ yìí yóo mú kí adùn ayé rẹ sọjí, yóo sì jẹ́ olùtọ́jú fún ọ ní ọjọ́ ogbó rẹ, nítorí iyawo ọmọ rẹ tí ó fẹ́ràn rẹ, tí ó sì ju ọmọkunrin meje lọ ni ó bímọ fún ọ.”
16. Naomi bá gba ọmọ náà, ó tẹ́ ẹ sí àyà rẹ̀, ó sì di olùtọ́jú rẹ̀.
17. Àwọn obinrin àdúgbò bá sọ ọmọ náà ní Obedi, wọ́n ń sọ káàkiri pé, “A bí ọmọkunrin kan fún Naomi.” Obedi yìí ni baba Jese tíí ṣe baba Dafidi.
18. Àwọn atọmọdọmọ Peresi nìwọ̀nyí: Peresi ni baba Hesironi;
19. Hesironi bí Ramu, Ramu bí Aminadabu;
20. Aminadabu bí Naṣoni; Naṣoni bí Salimoni;
21. Salimoni bí Boasi, Boasi bí Obedi;
22. Obedi bí Jese, Jese sì bí Dafidi.