Rutu 4:15-22 BIBELI MIMỌ (BM)

15. Ọmọ yìí yóo mú kí adùn ayé rẹ sọjí, yóo sì jẹ́ olùtọ́jú fún ọ ní ọjọ́ ogbó rẹ, nítorí iyawo ọmọ rẹ tí ó fẹ́ràn rẹ, tí ó sì ju ọmọkunrin meje lọ ni ó bímọ fún ọ.”

16. Naomi bá gba ọmọ náà, ó tẹ́ ẹ sí àyà rẹ̀, ó sì di olùtọ́jú rẹ̀.

17. Àwọn obinrin àdúgbò bá sọ ọmọ náà ní Obedi, wọ́n ń sọ káàkiri pé, “A bí ọmọkunrin kan fún Naomi.” Obedi yìí ni baba Jese tíí ṣe baba Dafidi.

18. Àwọn atọmọdọmọ Peresi nìwọ̀nyí: Peresi ni baba Hesironi;

19. Hesironi bí Ramu, Ramu bí Aminadabu;

20. Aminadabu bí Naṣoni; Naṣoni bí Salimoni;

21. Salimoni bí Boasi, Boasi bí Obedi;

22. Obedi bí Jese, Jese sì bí Dafidi.

Rutu 4