Peteru Kinni 1:21-25 BIBELI MIMỌ (BM)

21. Ẹ̀yin tí ẹ ti ipasẹ̀ rẹ̀ gba Ọlọrun tí ó jí i dìde kúrò ninu òkú gbọ́, tí ó ṣe é lógo, kí igbagbọ ati ìrètí yín lè wà ninu Ọlọrun.

22. Níwọ̀n ìgbà tí ẹ ti wẹ ọkàn yín mọ́ nípa ìgbọràn sí òtítọ́, tí ẹ sì ní ìfẹ́ àìlẹ́tàn sí àwọn onigbagbọ ara yín, ẹ fi tinútinú fẹ́ràn ọmọnikeji yín.

23. A ti tún yín bí! Kì í ṣe èso tí ó lè bàjẹ́ ni a fi tún yín bí bíkòṣe èso tí kò lè bàjẹ́, tíí ṣe ọ̀rọ̀ Ọlọrun tí ó wà láàyè, tí ó sì wà títí.

24. Nítorí,“Gbogbo ẹlẹ́ran-ara dàbí Koríko,gbogbo ògo rẹ̀ dàbí òdòdó.Koríko a máa gbẹ,òdòdó a máa rẹ̀,

25. ṣugbọn ọ̀rọ̀ Oluwa yóo wà títí lae.”Òun ni ọ̀rọ̀ tí à ń waasu rẹ̀ fun yín.

Peteru Kinni 1