Orin Solomoni 1:9-16 BIBELI MIMỌ (BM)

9. Olólùfẹ́ mi, mo fi ọ́ wé akọ ẹṣin tí ń fa kẹ̀kẹ́ ogun Farao.

10. Nǹkan ọ̀ṣọ́ mú kí ẹ̀rẹ̀kẹ́ rẹ lẹ́wà,ẹ̀gbà ọrùn sì mú kí ọrùn rẹ lẹ́wà.

11. A óo ṣe àwọn nǹkan ọ̀ṣọ́ wúrà,tí a fi fadaka ṣe ọnà sí lára fún ọ.

12. Nígbà tí ọba rọ̀gbọ̀kú lórí ìjókòó rẹ̀,turari mi ń tú òórùn dídùn jáde.

13. Olùfẹ́ mi dàbí àpò òjíá,bí ó ti sùn lé mi láyà.

14. Olùfẹ́ mi dàbí ìdì òdòdó igi Sipirẹsi,ninu ọgbà àjàrà Engedi.

15. Wò ó! O mà dára o, olólùfẹ́ mi;o lẹ́wà pupọ.Ojú rẹ tutù bíi ti àdàbà.

16. Háà, o mà dára o! Olùfẹ́ mi,o lẹ́wà gan-an ni.Ewéko tútù ni yóo jẹ́ ibùsùn wa.

Orin Solomoni 1