Orin Dafidi 90:11-14 BIBELI MIMỌ (BM)

11. Ta ló mọ agbára ibinu rẹ?Ta ló sì mọ̀ pé bí ẹ̀rù rẹ ti tó bẹ́ẹ̀ ni ibinu rẹ rí?

12. Nítorí náà kọ́ wa láti máa ka iye ọjọ́ orí wa,kí á lè kọ́gbọ́n.

13. Yipada sí wa, OLUWA; yóo ti pẹ́ tó tí o óo máa bínú sí wa?Ṣàánú àwa iranṣẹ rẹ.

14. Fi ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀ tẹ́ wa lọ́rùn ní òwúrọ̀,kí á lè máa yọ̀, kí inú wa sì máa dùnní gbogbo ọjọ́ ayé wa.

Orin Dafidi 90