Orin Dafidi 81:13-16 BIBELI MIMỌ (BM)

13. Àwọn eniyan mi ìbá jẹ́ gbọ́ tèmi,àní Israẹli ìbá jẹ́ máa rìn ní ọ̀nà mi!

14. Kíákíá ni èmi ìbá kọjú ìjà sí àwọn ọ̀tá wọn,tí ǹ bá sì ṣẹgun wọn.

15. Àwọn tí ó kórìíra OLUWA yóo fi ìbẹ̀rùbojo tẹríba fún un,ìyà óo sì jẹ wọ́n títí lae.

16. Ṣugbọn èmi ó máa fi ọkà tí ó dára jùlọ bọ yín,n óo sì fi oyin inú àpáta tẹ yín lọ́rùn.”

Orin Dafidi 81