Orin Dafidi 68:27-31 BIBELI MIMỌ (BM)

27. Ẹ wo Bẹnjamini tí ó kéré jù níwájú,ẹ wo ogunlọ́gọ̀ àwọn ìjòyè Juda,ẹ wo àwọn ìjòyè Sebuluni ati ti Nafutali.

28. Fi agbára rẹ hàn, Ọlọrun,fi agbára tí o ti fi jà fún wa hàn.

29. Nítorí Tẹmpili rẹ tí ó wà ní Jerusalẹmu,àwọn ọba yóo gbé ẹ̀bùn wá fún ọ.

30. Bá àwọn ẹranko ẹ̀dá tí ń gbé inú èèsún ní Ijipti wí;àwọn akọ mààlúù, láàrin agbo ẹran àwọn orílẹ̀-èdè.Tẹ àwọn tí ó fẹ́ràn owó mọ́lẹ̀;fọ́n àwọn orílẹ̀-èdè tí ó fẹ́ràn ogun ká.

31. Jẹ́ kí àwọn ikọ̀ wá láti Ijipti,kí àwọn ará Kuṣi tẹ́wọ́ adura sí Ọlọrun.

Orin Dafidi 68