Orin Dafidi 64:4-7 BIBELI MIMỌ (BM)

4. wọ́n ń sọ̀kò ọ̀rọ̀ sí aláìṣẹ̀ láti ibùba wọn,láìbẹ̀rù, wọ́n ń ta ọfà ọ̀rọ̀ sí i lójijì.

5. Wọ́n wonkoko mọ́ ète burúkú wọn;wọ́n ń gbìmọ̀ àtidẹ okùn sílẹ̀ níkọ̀kọ̀,wọ́n ń rò lọ́kàn wọn pé, “Ta ni yóo rí wa?

6. Ta ni yóo wá ẹ̀ṣẹ̀ wa rí?Ọgbọ́n àlùmọ̀kọ́rọ́yí ni a ti fi pète.”Áà, inú ọmọ eniyan jìn!

7. Ṣugbọn Ọlọrun yóo ta wọ́n lọ́fà;wọn óo fara gbọgbẹ́ lójijì.

Orin Dafidi 64