Orin Dafidi 58:2-6 BIBELI MIMỌ (BM)

2. Rárá o! Ibi ni ẹ̀ ń fi ọkàn yín rò,iṣẹ́ burúkú ni ẹ sì ń fi ọwọ́ yín ṣe láyé.

3. Láti inú oyún ni àwọn eniyan burúkú ti ṣìnà,láti ọjọ́ tí a ti bí wọn ni wọ́n tí ń ṣìṣe,tí wọn ń purọ́.

4. Wọ́n ní oró bí oró ejò,wọ́n dití bíi paramọ́lẹ̀ tí ó di etí ara rẹ̀,

5. kí ó má baà gbọ́ ohùn afunfèrè,tabi ìpè adáhunṣe.

6. Kán eyín mọ́ wọn lẹ́nu, Ọlọrun;OLUWA! Yọ ọ̀gàn àwọn ẹgbọ̀rọ̀ kinniun.

Orin Dafidi 58