Orin Dafidi 56:1-4 BIBELI MIMỌ (BM)

1. Ṣàánú mi, Ọlọrun, nítorí pé àwọn eniyan ń lépa mi;ọ̀tá gbógun tì mí tọ̀sán-tòru.

2. Àwọn ọ̀tá ń lépa mi tọ̀sán-tòru,ọpọlọpọ ní ń bá mi jà tìgbéraga-tìgbéraga.

3. Nígbà tí ẹ̀rù bá ń bà mí,èmi yóo gbẹ́kẹ̀lé ọ.

4. Ọlọrun, mo yìn ọ́ fún ọ̀rọ̀ rẹ,ìwọ ni mo gbẹ́kẹ̀lé láìbẹ̀rù;kí ni eniyan ẹlẹ́ran ara lè fi mí ṣe?

Orin Dafidi 56