10. Dáwọ́ ẹgba rẹ dúró lára mi,mo ti fẹ́rẹ̀ kú nítorí ìyà tí o fi ń jẹ mí.
11. Nígbà tí o bá jẹ eniyan níyàpẹlu ìbáwí nítorí ẹ̀ṣẹ̀,ìwọ á ba ohun tí ó ṣọ̀wọ́n fún un jẹ́ bíi kòkòrò aṣọ.Dájúdájú, afẹ́fẹ́ lásán ni eniyan.
12. “OLUWA, gbọ́ adura mi,tẹ́tí sí igbe mi,má dágunlá sí ẹkún mi,nítorí pé àlejò rẹ, tí ń rékọjá lọ ni mo jẹ́;àjèjì sì ni mí, bíi gbogbo àwọn baba mi.