Orin Dafidi 38:17-22 BIBELI MIMỌ (BM)

17. Nítorí pé mo ti fẹ́rẹ̀ ṣubú,mo sì wà ninu ìrora nígbà gbogbo.

18. Mo jẹ́wọ́ àṣìṣe mi,mo sì káàánú fún ẹ̀ṣẹ̀ mi.

19. Àwọn tí ń bá mi ṣọ̀tá láìnídìí lágbára,àwọn tí ó kórìíra mi láìtọ́ sì pọ̀.

20. Àwọn tí ń fi ibi san oore fún mi ní ń gbógun tì mí,nítorí pé rere ni mò ń ṣe.

21. OLUWA, má kọ̀ mí sílẹ̀,Ọlọrun mi, má jìnnà sí mi.

22. Yára wá ràn mí lọ́wọ́, OLUWA, ìgbàlà mi.

Orin Dafidi 38