Orin Dafidi 37:1-5 BIBELI MIMỌ (BM)

1. Má gbé ara rẹ lọ́kàn gbóná nítorí àwọn eniyan burúkú;má sì jowú àwọn aṣebi;

2. nítorí pé kíákíá ni wọn yóo gbẹ bí i koríko;wọn óo sì rọ bí ewé.

3. Gbẹ́kẹ̀lé OLUWA; kí o sì máa ṣe rere.Máa gbe ilẹ̀ náà; ewu kò sì ní wu ọ́.

4. Jẹ́ kí inú rẹ máa dùn ninu OLUWA;yóo sì fún ọ ní ohun tí ọkàn rẹ ń fẹ́.

5. Fi ọ̀nà rẹ lé OLUWA lọ́wọ́;gbẹ́kẹ̀lé e, yóo sì ṣe ohun tí ó yẹ.

Orin Dafidi 37