Orin Dafidi 32:7-10 BIBELI MIMỌ (BM)

7. Ìwọ ni ibi ìsásí mi;o pa mí mọ́ kúrò ninu ìṣòro;o sì fi ìgbàlà yí mi ká.

8. N óo kọ́ ọ, n óo sì tọ́ ọ sí ọ̀nà tí o óo rìn;n óo máa gbà ọ́ ní ìmọ̀ràn;n óo sì máa mójútó ọ.

9. Má ṣe dàbí ẹṣin tabi ìbaaka,tí kò ni ọgbọ́n ninu,tí a gbọdọ̀ kó ìjánu sí lẹ́nukí ó tó lè gbọ́ ti oluwa rẹ̀.

10. Ìrora pọ̀ fún àwọn eniyan burúkú,ṣugbọn ìfẹ́ tí kì í yẹ̀ ni ó yí àwọn tí ó gbẹ́kẹ̀lé OLUWA ká.

Orin Dafidi 32