21. Ẹni ìyìn ni OLUWA, nítorí pé, lọ́nà ìyanu,ó fi ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ hàn mí,nígbà tí ilẹ̀ ká mi mọ́.
22. Ẹ̀rù bà mí, mo sì sọ pé,“A lé mi jìnnà kúrò ní iwájú rẹ.”Ṣugbọn o gbọ́ ẹ̀bẹ̀ minígbà tí mo ké pè ọ́ fún ìrànlọ́wọ́.
23. Ẹ fẹ́ràn OLUWA, gbogbo ẹ̀yin olódodo,OLUWA a máa ṣọ́ àwọn olóòótọ́,a sì máa san àlékún ẹ̀san fún àwọn agbéraga.
24. Ẹ múra gírí, kí ẹ sì mọ́kàn le,gbogbo ẹ̀yin tí ẹ gbẹ́kẹ̀lé OLUWA.