Orin Dafidi 137:7-9 BIBELI MIMỌ (BM)

7. OLUWA, ranti ohun tí àwọn ará Edomu ṣenígbà tí Jerusalẹmu bọ́ sọ́wọ́ ọ̀tá,tí wọn ń pariwo pé,“Ẹ wó o palẹ̀! Ẹ wó o palẹ̀! Ẹ wó o títí dé ìpìlẹ̀ rẹ̀.”

8. Babiloni! Ìwọ apanirun!Ayọ̀ ń bẹ fún ẹni tí ó bá gbẹ̀san lára rẹ,fún gbogbo ohun tí o ti ṣe sí wa!

9. Ayọ̀ ń bẹ fún ẹni tí ó bá kó àwọn ọmọ wẹ́wẹ́ rẹ,tí ó ṣán wọn mọ́ àpáta.

Orin Dafidi 137