13. Ẹni tí ó pín Òkun Pupa sí meji,nítorí pé ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae;
14. ó sì mú àwọn ọmọ Israẹli kọjá láàrin rẹ̀,nítorí pé ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae;
15. ṣugbọn ó bi Farao ati àwọn ọmọ ogunrẹ̀ ṣubú ninu Òkun Pupa,nítorí pé ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae.
16. Ẹni tí ó mú àwọn eniyan rẹ̀ la aṣálẹ̀ já,nítorí pé ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae;
17. ẹni tí ó pa àwọn ọba ńlá,nítorí pé ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae;
18. ó sì pa àwọn ọba olókìkí,nítorí pé ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae;
19. Sihoni ọba àwọn Amori,nítorí pé ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae;
20. ati Ogu ọba Baṣani,nítorí pé ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae.
21. Ó pín ilẹ̀ wọn fún àwọn eniyan rẹ̀,nítorí pé ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae;
22. ó fún àwọn ọmọ Israẹli, iranṣẹ rẹ̀,nítorí pé ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae.
23. Òun ni ó ranti wa ní ipò ìrẹ̀lẹ̀ wa,nítorí pé ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae;
24. ó sì gbà wá lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wa,nítorí pé ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae.
25. Ẹni tí ó pèsè oúnjẹ fún gbogbo ẹ̀dá alààyè,nítorí pé ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ wà títí lae.