17. Wọ́n létí, ṣugbọn wọn kò lè gbọ́ràn,bẹ́ẹ̀ ni kò sí èémí kan ní ẹnu wọn.
18. Àwọn tí ń ṣe wọ́n yóo dàbí wọn,ati gbogbo àwọn tí ó bá gbẹ́kẹ̀lé wọn.
19. Ẹ̀yin ọmọ Israẹli, ẹ yin OLUWA,ẹ̀yin ará ilé Aaroni, ẹ yin OLUWA!
20. Ẹ̀yin ará ilé Lefi, ẹ yin OLUWA,ẹ̀yin tí ẹ bẹ̀rù OLUWA, ẹ yìn ín!
21. Ẹ yin OLUWA ní Sioni,ẹni tí ń gbé Jerusalẹmu!Ẹ yin OLUWA!