Orin Dafidi 135:17-21 BIBELI MIMỌ (BM)

17. Wọ́n létí, ṣugbọn wọn kò lè gbọ́ràn,bẹ́ẹ̀ ni kò sí èémí kan ní ẹnu wọn.

18. Àwọn tí ń ṣe wọ́n yóo dàbí wọn,ati gbogbo àwọn tí ó bá gbẹ́kẹ̀lé wọn.

19. Ẹ̀yin ọmọ Israẹli, ẹ yin OLUWA,ẹ̀yin ará ilé Aaroni, ẹ yin OLUWA!

20. Ẹ̀yin ará ilé Lefi, ẹ yin OLUWA,ẹ̀yin tí ẹ bẹ̀rù OLUWA, ẹ yìn ín!

21. Ẹ yin OLUWA ní Sioni,ẹni tí ń gbé Jerusalẹmu!Ẹ yin OLUWA!

Orin Dafidi 135