Orin Dafidi 119:91-95 BIBELI MIMỌ (BM)

91. Ohun gbogbo wà gẹ́gẹ́ bí ìlànà rẹ, títí di òní,nítorí pé iranṣẹ rẹ ni gbogbo wọn.

92. Bí kò bá jẹ́ pé òfin rẹ jẹ́ ìdùnnú mi,ǹ bá ti ṣègbé ninu ìpọ́njú.

93. Lae, n kò ní gbàgbé ẹ̀kọ́ rẹ,nítorí pé, nípasẹ̀ wọn ni o fi mú mi wà láyé.

94. Ìwọ ni o ni mí, gbà mí;nítorí pé mo ti kọ́ ẹ̀kọ́ rẹ.

95. Àwọn eniyan burúkú ba dè mí,wọ́n fẹ́ pa mí run,ṣugbọn mò ń ṣe àṣàrò lórí òfin rẹ.

Orin Dafidi 119