Orin Dafidi 119:53-58 BIBELI MIMỌ (BM)

53. Inú mi á máa ru,nígbà tí mo bá rí àwọn eniyan burúkú,tí wọn ń rú òfin rẹ.

54. Òfin rẹ ni mò ń fi ń ṣe orin kọ,lákòókò ìrìn àjò mi láyé.

55. Mo ranti orúkọ rẹ lóru;OLUWA, mo sì pa òfin rẹ mọ́:

56. Èyí ni ìṣe mi:Èmi a máa pa òfin rẹ mọ́.

57. OLUWA, ìwọ nìkan ni mo ní;mo ṣe ìlérí láti pa òfin rẹ mọ́.

58. Tọkàntọkàn ni mò ń wá ojurere rẹ,ṣe mí lóore gẹ́gẹ́ bí ìlérí rẹ.

Orin Dafidi 119