Orin Dafidi 119:27-38 BIBELI MIMỌ (BM)

27. La òfin rẹ yé mi,n óo sì máa ṣe àṣàrò lórí iṣẹ́ ìyanu rẹ.

28. Ìrẹ̀wẹ̀sì bá ọkàn mi nítorí ìbànújẹ́,mú mi lọ́kàn le gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.

29. Mú ìwà èké jìnnà sí mi,kí o sì fi oore ọ̀fẹ́ kọ́ mi ní òfin rẹ.

30. Mo ti yan ọ̀nà òtítọ́,mo ti fi ọkàn sí òfin rẹ.

31. Mo pa òfin rẹ mọ́, OLUWA,má jẹ́ kí ojú ó tì mí.

32. N óo yára láti pa òfin rẹ mọ́,nígbà tí o bá mú òye mi jinlẹ̀ sí i.

33. OLUWA, kọ́ mi ní ìlànà rẹ,n óo sì pa wọ́n mọ́ dé òpin.

34. Là mí lóye, kí n lè máa pa òfin rẹ mọ́,kí n sì máa fi tọkàntọkàn pa wọ́n mọ́.

35. Tọ́ mi sí ọ̀nà nípa òfin rẹ,nítorí pé mo láyọ̀ ninu rẹ̀.

36. Mú kí ọkàn mi fà sí òfin rẹ,kí ó má fà sí ọrọ̀ ayé.

37. Yí ojú mi kúrò ninu wíwo nǹkan asán,sọ mí di alààyè ní ọ̀nà rẹ.

38. Mú ìlérí rẹ ṣẹ fún iranṣẹ rẹ,àní, ìlérí tí o ṣe fún àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ.

Orin Dafidi 119