Orin Dafidi 119:24-33 BIBELI MIMỌ (BM)

24. Àwọn òfin rẹ ni dídùn inú mi,àwọn ni olùdámọ̀ràn mi.

25. Mo di ẹni ilẹ̀,sọ mí di alààyè gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.

26. Nígbà tí mo jẹ́wọ́ gbogbo ìṣe mi, o dá mi lóhùn;kọ́ mi ní ìlànà rẹ.

27. La òfin rẹ yé mi,n óo sì máa ṣe àṣàrò lórí iṣẹ́ ìyanu rẹ.

28. Ìrẹ̀wẹ̀sì bá ọkàn mi nítorí ìbànújẹ́,mú mi lọ́kàn le gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.

29. Mú ìwà èké jìnnà sí mi,kí o sì fi oore ọ̀fẹ́ kọ́ mi ní òfin rẹ.

30. Mo ti yan ọ̀nà òtítọ́,mo ti fi ọkàn sí òfin rẹ.

31. Mo pa òfin rẹ mọ́, OLUWA,má jẹ́ kí ojú ó tì mí.

32. N óo yára láti pa òfin rẹ mọ́,nígbà tí o bá mú òye mi jinlẹ̀ sí i.

33. OLUWA, kọ́ mi ní ìlànà rẹ,n óo sì pa wọ́n mọ́ dé òpin.

Orin Dafidi 119