Orin Dafidi 119:164-169 BIBELI MIMỌ (BM)

164. Nígbà meje lojoojumọ ni mò ń yìn ọ́nítorí òfin òdodo rẹ.

165. Alaafia ńláńlá ń bẹ fún àwọn tí ó fẹ́ràn òfin rẹ,kò sí ohun tí ó lè mú wọn kọsẹ̀.

166. Mò ń retí ìgbàlà rẹ, OLUWA,mo sì ń pa àwọn òfin rẹ mọ́.

167. Mò ń pa àṣẹ rẹ mọ́,mo fẹ́ràn wọn gidigidi.

168. Mo gba ẹ̀kọ́ rẹ, mo sì ń tẹ̀lé ìlànà rẹ;gbogbo ìṣe mi ni ò ń rí.

169. Jẹ́ kí igbe mi dé ọ̀dọ̀ rẹ, OLUWA,fún mi ní òye gẹ́gẹ́ bí ìlérí rẹ.

Orin Dafidi 119