Orin Dafidi 119:148-153 BIBELI MIMỌ (BM)

148. N kò fi ojú ba oorun ní gbogbo òru,kí n lè máa ṣe àṣàrò lórí ọ̀rọ̀ rẹ.

149. Gbóhùn mi nítorí ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀,OLÚWA, dá mi sí nítorí òtítọ́ rẹ.

150. Àwọn tí ń ṣe inúnibíni mi súnmọ́ tòsí;wọ́n jìnnà sí òfin rẹ.

151. Ṣugbọn ìwọ wà nítòsí, OLUWA,òtítọ́ sì ni gbogbo òfin rẹ.

152. Ó pẹ́ tí mo ti kọ́ ninu ìlànà rẹ,pé o ti fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀ títí lae.

153. Wo ìpọ́njú mi, kí o gbà mí,nítorí n kò gbàgbé òfin rẹ.

Orin Dafidi 119