Orin Dafidi 119:141-148 BIBELI MIMỌ (BM)

141. Bí mo tilẹ̀ kéré, tí ayé sì kẹ́gàn mi,sibẹ n kò gbàgbé ìlànà rẹ.

142. Òdodo rẹ wà títí lae,òtítọ́ sì ni òfin rẹ.

143. Ìyọnu ati ìpayà dé bá mi,ṣugbọn mo láyọ̀ ninu òfin rẹ.

144. Òdodo ni ìlànà rẹ títí lae,fún mi ní òye kí n lè wà láàyè.

145. Tọkàntọkàn ni mo fi ń ké pè ọ́,OLUWA, dá mi lóhùn;n óo sì máa tẹ̀lé ìlànà rẹ.

146. Mo ké pè ọ́; gbà mí,n óo sì máa mú àṣẹ rẹ ṣẹ.

147. Mo jí ní òwúrọ̀ kutukutu, mo sì kígbe fún ìrànlọ́wọ́;mò ń retí ìmúṣẹ ọ̀rọ̀ rẹ.

148. N kò fi ojú ba oorun ní gbogbo òru,kí n lè máa ṣe àṣàrò lórí ọ̀rọ̀ rẹ.

Orin Dafidi 119