Orin Dafidi 119:103-108 BIBELI MIMỌ (BM)

103. Ọ̀rọ̀ rẹ dùn mọ́ mi pupọ,ó dùn ju oyin lọ.

104. Nípa ẹ̀kọ́ rẹ ni mo fi ní òye,nítorí náà mo kórìíra gbogbo ìwà èké.

105. Ọ̀rọ̀ rẹ ni àtùpà fún ẹsẹ̀ mi,òun ni ìmọ́lẹ̀ sí ọ̀nà mi.

106. Mo ti búra, n óo sì mú un ṣẹ,pé n óo máa pa òfin òdodo rẹ mọ́.

107. Ojú ń pọ́n mi lọpọlọpọ,sọ mí di alààyè, OLUWA, gẹ́gẹ́ bí ìlérí rẹ.

108. Gba ẹbọ ìyìn àtọkànwá mi, OLUWA,kí o sì kọ́ mi ní ìlànà rẹ.

Orin Dafidi 119