Orin Dafidi 119:101-110 BIBELI MIMỌ (BM)

101. N kò rin ọ̀nà ibi kankan,kí n lè pa òfin rẹ mọ́.

102. N kò yapa kúrò ninu òfin rẹ,nítorí pé o ti kọ́ mi.

103. Ọ̀rọ̀ rẹ dùn mọ́ mi pupọ,ó dùn ju oyin lọ.

104. Nípa ẹ̀kọ́ rẹ ni mo fi ní òye,nítorí náà mo kórìíra gbogbo ìwà èké.

105. Ọ̀rọ̀ rẹ ni àtùpà fún ẹsẹ̀ mi,òun ni ìmọ́lẹ̀ sí ọ̀nà mi.

106. Mo ti búra, n óo sì mú un ṣẹ,pé n óo máa pa òfin òdodo rẹ mọ́.

107. Ojú ń pọ́n mi lọpọlọpọ,sọ mí di alààyè, OLUWA, gẹ́gẹ́ bí ìlérí rẹ.

108. Gba ẹbọ ìyìn àtọkànwá mi, OLUWA,kí o sì kọ́ mi ní ìlànà rẹ.

109. Ayé mi wà ninu ewu nígbà gbogbo,ṣugbọn n kò gbàgbé òfin rẹ.

110. Àwọn eniyan burúkú ti dẹ okùn sílẹ̀ dè mí,ṣugbọn n kò kọ ìlànà rẹ sílẹ̀.

Orin Dafidi 119