Orin Dafidi 115:9-16 BIBELI MIMỌ (BM)

9. Ẹ̀yin ọmọ Israẹli, ẹ gbẹ́kẹ̀lé OLUWA,òun ni olùrànlọ́wọ́ ati aláàbò yín.

10. Ẹ̀yin ìdílé Aaroni, ẹ gbẹ́kẹ̀lé OLUWA,òun ni olùrànlọ́wọ́ ati aláàbò yín.

11. Ẹ̀yin tí ẹ bẹ̀rù OLUWA, ẹ gbẹ́kẹ̀lé e,òun ni olùrànlọ́wọ́ ati aláàbò yín.

12. OLUWA ranti wa, yóo bukun wa,yóo bukun ilé Israẹli,yóo bukun ìdílé Aaroni.

13. Yóo bukun àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀,ati àwọn ọlọ́lá ati àwọn mẹ̀kúnnù.

14. OLUWA yóo jẹ́ kí ẹ máa bí sí i,àtẹ̀yin àtàwọn ọmọ yín.

15. Kí OLUWA tí ó dá ọ̀run ati ayé bukun yín!

16. OLUWA ló ni ọ̀run,ṣugbọn ó fi ayé fún àwọn eniyan.

Orin Dafidi 115