Nọmba 35:18-23 BIBELI MIMỌ (BM)

18. Tabi tí ó bá fi ohun ìjà olóró lu arakunrin rẹ̀ tí ẹni náà sì kú, apànìyàn ni, pípa ni wọn yóo pa òun náà.

19. Arakunrin ẹni tí a pa ni yóo pa apànìyàn náà nígbà tí ó bá rí i.

20. “Bí ẹnìkan bá kórìíra arakunrin rẹ̀, tí ó sì fi ohun ìjà gún un, tabi tí ó ju nǹkan lù ú láti ibi tí ó sápamọ́ sí, tí ẹni náà bá kú,

21. tabi tí ó fi ọwọ́ rẹ̀ lù ú pẹlu ibinu tí ẹni náà sì kú. Apànìyàn náà yóo jẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ ìpànìyàn, yóo sì kú fún ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀. Arakunrin ẹni tí ó pa ni yóo pa apànìyàn náà nígbà tí ó bá rí i.

22. “Ṣugbọn bí ẹnìkan bá ṣèèṣì paniyan, tí kì í ṣe pẹlu ìríra, kì báà jẹ́ pé ó fi ohun ìjà gún un, tabi kí ó ṣèèṣì ju nǹkan lù ú,

23. tabi bí ẹnìkan bá ṣèèṣì sọ òkúta láì wo ibi tí ó sọ òkúta náà sí, tí òkúta náà sì pa eniyan tí kì í ṣe pé ó ti fẹ́ pa olúwarẹ̀ tẹ́lẹ̀, tí kò sì kórìíra rẹ̀,

Nọmba 35