Nọmba 34:15-20 BIBELI MIMỌ (BM)

15. ní ìhà ìlà oòrùn Jọdani ní òdìkejì Jẹriko. Wọ́n sì ti pín in ní ìdílé-ìdílé.”

16. OLUWA sọ fún Mose pé,

17. “Eleasari alufaa ati Joṣua ọmọ Nuni ni yóo pín ilẹ̀ náà fun yín.

18. Mú olórí kọ̀ọ̀kan ninu ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan láti ràn wọ́n lọ́wọ́.”

19. Àwọn olórí náà nìwọ̀nyí: láti inú ẹ̀yà Juda, a yan Kalebu ọmọ Jefune.

20. Láti inú ẹ̀yà Simeoni, a yan Ṣemueli ọmọ Amihudu.

Nọmba 34