Nọmba 26:40-46 BIBELI MIMỌ (BM)

40. Àwọn ọmọ Bela nìwọ̀nyí: ìdílé Aridi ati ìdílé Naamani.

41. Gbogbo àwọn tí a kà ninu ẹ̀yà Bẹnjamini jẹ́ ẹgbaa mejilelogun ó lé ẹgbẹjọ (45,600).

42. Àwọn ọmọ Dani ní ìdílé-ìdílé nìwọ̀nyí: ìdílé Ṣuhamu.

43. Gbogbo àwọn tí a kà ninu ẹ̀yà Dani jẹ́ ẹgbaa mejilelọgbọn ó lé irinwo (64,400).

44. Àwọn ọmọ Aṣeri ní ìdílé-ìdílé nìwọ̀nyí: ìdílé Imina, ìdílé Iṣifi ati ìdílé Beria.

45. Àwọn ọmọ Beria ni: ìdílé Heberi ati ìdílé Malikieli.

46. Orúkọ ọmọ Aṣeri obinrin sì ni Sera.

Nọmba 26