9. Ṣugbọn a gbadura sí Ọlọrun wa, a sì yan àwọn olùṣọ́ láti máa ṣọ́ ibẹ̀ tọ̀sán-tòru.
10. Àwọn ará Juda bẹ̀rẹ̀ sí kọrin pé,“Agbára àwa tí à ń ṣe iṣẹ́ ń dín kù,iṣẹ́ sì tún pọ̀ nílẹ̀;ǹjẹ́ a ó lè mọ odi náà mọ́ báyìí?”
11. Àwọn ọ̀tá wa sì wí pé, “Wọn kò ní mọ ohun tí ń ṣẹlẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò ní rí wa títí tí a óo fi dé ọ̀dọ̀ wọn, tí a óo pa wọ́n, tí iṣẹ́ náà yóo sì dúró.”