7. “Nígbà tí ẹ bá ń gbadura, ẹ má máa wí nǹkankan náà títí, bí àwọn abọ̀rìṣà ti ń ṣe. Nítorí wọ́n rò pé nípa ọ̀rọ̀ pupọ ni adura wọn yóo ṣe gbà.
8. Ẹ má ṣe fara wé wọn, nítorí Baba yín ti mọ ohun tí ẹ nílò kí ẹ tó bèèrè lọ́wọ́ rẹ̀.
9. Nítorí náà, báyìí ni kí ẹ̀yin máa gbadura:‘Baba wa tí ń bẹ ní ọ̀run:Kí á bọ̀wọ̀ fún orúkọ mímọ́ rẹ,