Luku 1:68-74 BIBELI MIMỌ (BM)

68. Kí á yin Oluwa Ọlọrun Israẹlinítorí ó ti mú ìrànlọ́wọ́ wá fún àwọn eniyan rẹ̀,ó sì ti dá wọn nídè.

69. Ó ti gbé Olùgbàlà dìde fún waní ìdílé Dafidi, iranṣẹ rẹ̀;

70. gẹ́gẹ́ bí ó ti sọ láti ẹnu àwọn wolii rẹ̀ mímọ́,láti ọjọ́ pípẹ́;

71. pé yóo gbà wá lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá waati lọ́wọ́ gbogbo àwọn tí ó kórìíra wa;

72. pé yóo fi àánú bá àwọn baba wa lò,ati pé yóo ranti majẹmu rẹ̀ mímọ́

73. gẹ́gẹ́ bí ó ti búra fún Abrahamu baba wa,

74. pé yóo gbà wá lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wa,ati pé yóo fún wa ní anfaani láti máa sìn ín láì fòyà,

Luku 1