46. Nígbà náà ni Maria sọ pé,“Ọkàn mi gbé Oluwa ga,
47. ẹ̀mí mi yọ̀ sí Ọlọrun, Olùgbàlà mi,
48. nítorí ó ti bojúwo ipò ìrẹ̀lẹ̀ iranṣẹbinrin rẹ̀.Wò ó! Láti ìgbà yìí lọgbogbo ìran ni yóo máa pè mí ní olóríire.
49. Nítorí Olodumare ti ṣe ohun ńlá fún mi,Mímọ́ ni orúkọ rẹ̀;
50. àánú rẹ̀ sì wà láti ìran dé ìranfún àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀.