Luku 1:46-50 BIBELI MIMỌ (BM)

46. Nígbà náà ni Maria sọ pé,“Ọkàn mi gbé Oluwa ga,

47. ẹ̀mí mi yọ̀ sí Ọlọrun, Olùgbàlà mi,

48. nítorí ó ti bojúwo ipò ìrẹ̀lẹ̀ iranṣẹbinrin rẹ̀.Wò ó! Láti ìgbà yìí lọgbogbo ìran ni yóo máa pè mí ní olóríire.

49. Nítorí Olodumare ti ṣe ohun ńlá fún mi,Mímọ́ ni orúkọ rẹ̀;

50. àánú rẹ̀ sì wà láti ìran dé ìranfún àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀.

Luku 1